[Chorus]
Ẹ wá, ẹ jẹ́ ká yin Olúwa Ọlọ́run mi,
Oore-ọ̀fẹ́ Rẹ̀ ló mú wa dé òní;
Ó fọ́ ìdè irin,
Ó ṣẹ́gun ikú,
Èmi yóò máa jó, èmi yóò máa kọrin,
Màá fi iyìn fún orúkọ Rẹ.
[Veese 1]
Tẹ́lẹ̀ mo ti kú nínú ẹ̀ṣẹ̀,
Ṣùgbọ́n Jèhófà rán Jésù Kristi;
Ó rà mí padà kúrò lọ́wọ́ ikú,
Ó sì gbà mí kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀;
Èmi yóò máa jó, èmi yóò máa kọrin,
Màá fi iyìn fún orúkọ Rẹ.
[Chorus]
Ẹ wá, ẹ jẹ́ ká yin Olúwa Ọlọ́run mi,
Oore-ọ̀fẹ́ Rẹ̀ ló mú wa dé òní;
Ó fọ́ ìdè irin,
Ó ṣẹ́gun ikú,
Èmi yóò máa jó, èmi yóò máa kọrin,
Màá fi iyìn fún orúkọ Rẹ.
[Verse 2]
Kí ni màá fi san fún Ọ, Baba?
Wúrà ati fàdákà kò yẹ́ fún Ọ;
Bí mo bá sè oúnjẹ fún Ọ,
Iwọ kì í jẹun bí ènìyàn;
Ìyìn nikan l'O bèrè lọ́wọ́ mi,
Èmi yóò máa jó, èmi yóò máa kọrin,
Màá fi iyìn fún orúkọ Rẹ.
[Chorus]
Ẹ wá, ẹ jẹ́ ká yin Olúwa Ọlọ́run mi,
Oore-ọ̀fẹ́ Rẹ̀ ló mú wa dé òní;
Ó fọ́ ìdè irin,
Ó ṣẹ́gun ikú,
Èmi yóò máa jó, èmi yóò máa kọrin,
Màá fi iyìn fún orúkọ Rẹ.
[Verse 3]
Mi ò tíì rí Ọlọ́run bí Iwọ,
Tó ń ṣe iṣẹ́ ìyanu nlá;
Ọwọ́ Rẹ̀ ń gbà àwọn ọmọ Rẹ là,
Lójoojúmọ́ O ń ṣe ìgbàlà;
Ìbá ṣe pé ayé mọ rírì Rẹ,
Èmi yóò máa jó, èmi yóò máa kọrin,
Màá fi iyìn fún orúkọ Rẹ.
[Chorus]
Ẹ wá, ẹ jẹ́ ká yin Olúwa Ọlọ́run mi,
Oore-ọ̀fẹ́ Rẹ̀ ló mú wa dé òní;
Ó fọ́ ìdè irin,
Ó ṣẹ́gun ikú,
Èmi yóò máa jó, èmi yóò máa kọrin,
Màá fi iyìn fún orúkọ Rẹ.
[Verse 4]
Nígbà tí mo wà láyé yìí,
Mi ò ní dá íyin Rẹ dúró;
Nígbà tí ẹ̀mí ṣì wà lára mi,
Èmi yóò máa yin Ọ lálẹ́ at'òru;
Ohunkóhun tí ówù tíì bá jẹ́,
Èmi yóò máa jó, èmi yóò máa kọrin,
Màá fi iyìn fún orúkọ Rẹ.
[Chorus]
Ẹ wá, ẹ jẹ́ ká yin Olúwa Ọlọ́run mi,
Oore-ọ̀fẹ́ Rẹ̀ ló mú wa dé òní;
Ó fọ́ ìdè irin,
Ó ṣẹ́gun ikú,
Èmi yóò máa jó, èmi yóò máa kọrin,
Màá fi iyìn fún orúkọ Rẹ.
[Verse 5]
Ayé mi kò ní ìtumọ̀ láìsí Rẹ,
Ìwọ ni Ìbẹ̀rẹ̀ àti Òpin mi;
Bí ayé asán yìí bá ré kọjá,
Èmi yóò bá Ọ gbé títí láé;
Ní ayérayé màá máa yìn Ọ,
Èmi yóò máa jó, èmi yóò máa kọrin,
Màá fi iyìn fún orúkọ Rẹ.
[Chorus]
Ẹ wá, ẹ jẹ́ ká yin Olúwa Ọlọ́run mi,
Oore-ọ̀fẹ́ Rẹ̀ ló mú wa dé òní;
Ó fọ́ ìdè irin,
Ó ṣẹ́gun ikú,
Èmi yóò máa jó, èmi yóò máa kọrin,
Màá fi iyìn fún orúkọ Rẹ.
[Final Chorus]
Ẹ wá, ẹ jẹ́ ká yin Olúwa Ọlọ́run mi,
Oore-ọ̀fẹ́ Rẹ̀ ló mú wa dé òní;
Ó fọ́ ìdè irin,
Ó ṣẹ́gun ikú,
Èmi yóò máa jó, èmi yóò máa kọrin,
Màá fi iyìn fún orúkọ Rẹ.